ORIN DAFIDI 131
131
Àṣírí ìfọ̀kànbalẹ̀
1OLUWA, n kò ṣe ìgbéraga,
bẹ́ẹ̀ ni ojú mi kò gbé sókè.
N ò dáwọ́ lé nǹkan ńláńlá,
n ò sì dá àrà tí ó jù mí lọ.
2Kàkà bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi lọ́kàn balẹ̀, mo dákẹ́ jẹ́ẹ́,
bí ọmọ ọwọ́ tíí dákẹ́ jẹ́ẹ́ láyà ìyá rẹ̀.
Ọkàn mi balẹ̀ bíi ti ọmọ ọwọ́ tó dákẹ́ jẹ́ẹ́.
3Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ ní ìrètí ninu OLUWA,
láti ìsinsìnyìí lọ ati títí laelae.
Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:
ORIN DAFIDI 131: YCE
Ìsàmì-sí
Pín
Daako
![None](/_next/image?url=https%3A%2F%2Fimageproxy.youversionapi.com%2F58%2Fhttps%3A%2F%2Fweb-assets.youversion.com%2Fapp-icons%2Fyo.png&w=128&q=75)
Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀
Bible Society of Nigeria © 1900/2010