ORIN DAFIDI 121

121
OLUWA Aláàbò Wa
1Mo gbójú sókè wo àwọn òkè,
níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi ti ń wá?
2Ìrànlọ́wọ́ mi ń ti ọ̀dọ̀ OLUWA wá,
ẹni tí ó dá ọ̀run ati ayé.
3Kò ní jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ ó yẹ̀,
ẹni tí ń pa ọ́ mọ́ kò ní tòògbé.
4Wò ó, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́
kò ní tòògbé, bẹ́ẹ̀ ni kò ní sùn.
5OLUWA ni olùpamọ́ rẹ.
OLUWA yóo ṣíji bò ọ́ ní apá ọ̀tún rẹ.
6Oòrùn kò ní ṣe ọ́ léṣe lọ́sàn-án,
bẹ́ẹ̀ ni òṣùpá kò ní pa ọ́ lára lóru.
7OLUWA óo dáàbò bò ọ́ lọ́wọ́ gbogbo ibi,
yóo pa ọ́ mọ́.
8OLUWA yóo pa àlọ ati ààbọ̀ rẹ mọ́,
láti ìsinsìnyìí lọ ati títí lae.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 121: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀