AMOSI Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ọ̀rọ̀ Iṣaaju
Amosi ni wolii àkọ́kọ́ tí wọn kọ pupọ ninu iṣẹ́ tí ó jẹ́ sinu Bibeli. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ará ìlú kan ní Juda ni, ó waasu fún àwọn ará ìhà àríwá Israẹli ní nǹkan bí ẹgbẹrin ọdún kí á tó bí OLUWA wa, (8th century B.C.) Àkókò ìlọsíwájú ni àkókò Amosi, ó dàbí ẹni pé àwọn eniyan ń sin Ọlọrun tọkàntọkàn, ààbò tí ó dájú sì wà lórí wọn. Ṣugbọn Amosi ṣàkíyèsí pé, ọ̀dọ̀ àwọn ọlọ́rọ̀ ni ìlọsíwájú náà fì sí, ati pé wọ́n ń ni àwọn talaka lára, kò sì sí ìdájọ́ òdodo. Àwọn eniyan kò fi tọkàntọkàn ṣe ẹ̀sìn, ààbò kò sì dájú tó bí wọ́n ti lérò pé ó wà. Ó múra gírí, ó sì fi ìtara waasu pé Ọlọrun yóo jẹ orílẹ̀-èdè náà níyà. Ó rọ̀ wọ́n pé kí wọn jẹ́ kí ìdájọ́ òdodo, “máa ṣàn bí odò” ati pé “Bóyá OLUWA lè ṣàánú àwọn ará orílẹ̀-èdè yìí tí ó kù láàyè.” (5:15)
Àwọn Ohun tí ó wà ninu Ìwé yìí ní Ìsọ̀rí-ìsọ̀rí
Ìdájọ́ lórí àwọn tí ń gbé agbègbè Israẹli 1:1–2:5
Ìdájọ́ lórí Israẹli 2:6–6:14
Ìran marun-un 7:1–9:15

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

AMOSI Ọ̀rọ̀ Iṣaaju: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀