Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú Luk 2:11

Gbígbé nínú Jésù - Ètò-ẹ̀kọ́ Ìfọkànsìn Ọlọ́jọ́ Mẹ́rin lórí Ìwásáyé Jésù
Ọjọ́ Mẹ́rìn
Kérésìmesì ńbọ̀! Ó wá pẹ̀lú Ìwásáyé Jésù - ìmúrasílẹ̀ àti àjoyọ̀ ìbí Jésù. Sùgbọ́n njẹ́ ìmọ̀ yí kò ti sọnù nípasẹ̀ ìmúra ìsinmi ọdún, ríra ẹ̀bùn fún ọdún, tàbí ìgbàlejò àwọn ebí? Nínú lílọ sókè sódò àsìkò ọdún kérésìmesì, ní ìrírí titun nípa oríṣi ọ̀nà tí a lẹ gbà latí máa ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, èyí yíò sì fà ó súnmọ́ Ọlọ́run. Jí ọkàn rẹ dìde nínú ètò ọlọ́jọ́ mẹ́rin yìí láti inú àwọn àkójọ Bíbélì Gbé-Inú láti ọwọ́ Thomas Nelson.

Awọn itan keresimesi
Ọjọ́ 5
Gbogbo ìtàn gidi ló ní ìyípadà ìtàn - àkókò àìròtẹ́lẹ̀ tí ó yí gbogbo nǹkan padà. Ọ̀kan lára àwọn ìyípadà ìtàn tó tóbi jùlọ nínú Bíbélì ni ìtàn Kérésìmesì. Ní ọjọ́ márùn-ún tó ń bọ̀, a máa ṣàwárí bí ìṣẹ̀lẹ̀ kan yìí ṣe yí ayé padà àti bí ó ṣe lè yí ayé rẹ padà lónìí.

Ọgbẹ́ Ọkàn Dé: Ìrètí L'ásìkò Ìsinmi
Ọjọ marun
Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀, àkókò ìsinmi jẹ́ àkókò ayọ̀ ńlá...ṣùgbón kíni yío ṣẹlẹ̀ nígbàtí àkókò ìsinmi bá sọ adùn rẹ̀ nù tí ó bá sì di àkókò ìpèníjà látàrí ìbànújẹ́ tàbí àdánù ńlà? Ètò ẹ̀kọ́ pàtàkì yìí yíó ran àwọn tí ó ń la ìbànújẹ́ kọjá láti ṣàwárí ìtùnù àti ìrètí l'ákòkò ìsinmi, àti láti ṣ'àgbékalẹ̀ àkókò ìsinmi tó n'ítumọ̀ làì fi ti ìbànújẹ́ ọkàn ṣe.

Àṣàrò Nípa Kérésìmesì
Ọjọ́ Márùn-ún
Ìtàn Kérésìmesì wa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìkéde áńgẹ́lì sí Màríà ó sì parí pẹ̀lú ìbẹ̀wò àwọn amòye. Nínú àwọn àṣàrò wọ̀nyí àti àwọn àmúlò ti ìtàn àkọsílẹ̀ Kérésìmesì èmi yóò tọ́ka sí ìwé Lúùkú púpọ̀, nítorí ìwé tirẹ̀ ni ó kún jùlọ nínú àwọn àkọsílẹ̀ ìhìnrere.

Ìdí tí a fi bí Jésù
Ọjọ́ Márùn-ún
Kíni ìdí rẹ̀ tí a fi bí Jésù? Èyí lè jọ́ ìbéèrè tí ó rọrùn, tí ó wọ́pọ́ọ̀ tí à lè r'onú lé lórí. Ṣùgbọ́n bí o ti ń gbáradì fún Kérésìmesì ti ọdún yìí, tẹ ẹsè dúró díẹ̀ láti ṣe àṣàrò lórí ìtumọ̀ tí ó jinlẹ̀ àti ète ìbí Jésù fún ayé rẹ àti gbogbo àgbáyé. A kọ ètò ọlọ́jọ́ márùn-ún yìí láti ọwọ́ Scott Hoezee, ó sì jẹ́ àyọkà láti inú ẹ̀kọ́-ìfọkànsìn ojoojúmọ́ ti Words of Hope (Ọrọ̀ Ìrètí).

Bí ìgbé ayé ṣe yí padà: Ní àkókò Kérésìmesì
Ọjọ 5
Nínú gbogbo ìgbòkègbodò ọdún, ó ṣeéṣe kí a má kíyèsára ìdí tí a fi ń ṣe ayẹyẹ. Nínú ètò ọlọ́jọ́ márùn bíbọ̀ Oluwa yí a ó ṣe àgbéyẹ̀wò àwọn ìlérí tí ìbí Rẹ̀ mú wá sí ìmúṣẹ nípa bí a ṣe bí Jésù àti ìrètí tí a ní fún ọjọ́ iwájú. Bí a ṣe ń kẹ́kọ̀ sí í nípa ẹni tí Ọlọ́run jẹ́, a ó ṣe àwárí bí a ṣe lè máa gbé ní àkókò ìsinmi ọdún pẹ̀lú ìrètí, ìgbàgbọ́, ayọ̀, àti àlàáfíà.

Rin Ìrìn-Àjò Rẹ Láì Sí Ẹrú Wúwo
Ọjọ́ Méje
Ní àkókò pọ̀pọ̀sìnsìn ọ́dún Kérésì, ọ̀pọ̀lọpọ̀ wa ló máa ń fajúro nítorí wàhálà àti àníyàn tó jẹmọ́ ìbáṣepọ̀ pẹ̀lú ẹbí, làálàá ìṣúná, ìpinnu ìdágìrì àti ìjákulẹ̀ nípa àwọn ìrètí wa. Wàyì o, gbé ìgbésẹ. Mí kanlẹ̀. Bẹ̀rẹ̀ ètò Bíbélì Life.Church yí láti ní òye wípé ẹrù náà tó ń rìn wá mọ́lẹ̀ lè jẹ́ èyí tí Ọlọ́run kò rán wa láti gbé rárá. A ò bá jọ̀wọ́ ẹrù wúwo yìí. Jẹ́ kí a rin ìrìn àjò tó fúyẹ́.

KÉRÉSÌMESÌ: Ìmúṣẹ Ètò Ìdáǹdè Ọlọ́run
Ọjọ́ Mẹ́rìnlá
Àwọn òrìṣà èké tí àwọn ènìyàn mọ láti fi ṣe àpèjúwe òrìṣà kan tí wọ́n mọ̀ pé ó ní láti wà, kò ya'ni l'ẹ́nu pé, wọ́n jọ àwa ènìyàn gan-an. Wọ́n ní láti fi ìfọkànsìn mú wọn, kí wọ́n sì fún wọn ní rìbá kí wọ́n lè ṣe àkíyèsí wa. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà ti gbé ìgbésẹ̀, ó sì ń wá wa kiri––láti gbà wá padà sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀. Èyí gan-an ni ìtàn Kérésìmesì.

Oswald Chambers: Ìdùnnú - Agbára Nínú Olúwa
Ọgbọ̀n ọjọ́
Sàwárí òye ti Oswald Chambers, olùkọ̀wé Sísa gbogbo ipá fún Gíga jùlọ, nínú ìṣúra èyí òye inú nípa ìdùnnú. Àwon àyọlò ọ̀rọ̀ tún tayọ nínú èkó kíkà kọ̀ọ̀kan láti Chambers nírẹ̀ẹ́pọ̀ pèlú àwon ìbéèrè fún Ijiroro tiré gan. Bí ó se mísí o àti pè o níjà pèlú òyé rè tó rorùn àti òye Bíbèlí, wa a rí ara re n fé láti lo àkókò sí i ni bibá Olórun sòrò.