O. Daf 89:38-52
O. Daf 89:38-52 Bibeli Mimọ (YBCV)
Ṣugbọn iwọ ti ṣa tì, iwọ si korira, iwọ ti binu si Ẹni-ororo rẹ. Iwọ ti sọ majẹmu iranṣẹ rẹ di ofo: iwọ ti sọ ade rẹ̀ si ilẹ. Iwọ ti fa ọgba rẹ̀ gbogbo ya: iwọ ti mu ilu-olodi rẹ̀ di ahoro. Gbogbo awọn ti nkọja lọ li ọ̀na nfi ṣe ijẹ: on si di ẹ̀gan fun awọn aladugbo rẹ̀. Iwọ ti gbé ọwọ ọtún awọn ọta rẹ̀ soke; iwọ mu gbogbo awọn ọta rẹ̀ yọ̀. Iwọ si ti yi oju idà rẹ̀ pada pẹlu, iwọ kò si mu u duro li oju ogun. Iwọ ti mu ogo rẹ̀ tẹ́, iwọ si wọ́ itẹ́ rẹ̀ silẹ-yilẹ. Ọjọ ewe rẹ̀ ni iwọ ke kuru; iwọ fi itìju bò o. Yio ti pẹ to, Oluwa? iwọ o pa ara rẹ mọ́ lailai? ibinu rẹ yio ha jo bi iná bi? Ranti bi ọjọ mi ti kuru to; ẽse ti iwọ ha da gbogbo enia lasan? Ọkunrin wo li o wà lãye, ti kì yio ri ikú? ti yio gbà ọkàn rẹ̀ lọwọ isa-okú. Oluwa, nibo ni iṣeun-ifẹ rẹ atijọ wà, ti iwọ bura fun Dafidi ninu otitọ rẹ? Oluwa, ranti ẹ̀gan awọn iranṣẹ rẹ, ti emi nrù li aiya mi lati ọdọ gbogbo ọ̀pọ enia. Ti awọn ọta rẹ fi kẹgàn, Oluwa: ti nwọn fi ngàn ipasẹ Ẹni-ororo rẹ. Olubukún ni Oluwa si i titi lailai. Amin ati Amin.
O. Daf 89:38-52 Yoruba Bible (YCE)
Ṣugbọn nisinsinyii inú rẹ ti ru sí ẹni àmì òróró rẹ; o ti ta á nù, o sì ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀. O ti pa majẹmu tí o bá iranṣẹ rẹ dá tì, o ti ba adé rẹ̀ jẹ́, o ti fi wọ́lẹ̀. O ti wó gbogbo odi rẹ̀; o sì ti sọ ilé ìṣọ́ rẹ̀ di ahoro. Gbogbo àwọn tí ń kọjá lọ ní ń kó o lẹ́rù; ó ti di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn aládùúgbò rẹ̀. O ti ran àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́; o ti mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ yọ̀ ọ́. Àní, o ti ba gbogbo ohun ìjà rẹ̀ jẹ́, o kò sì ràn án lọ́wọ́ lójú ogun. O ti gba ọ̀pá àṣẹ lọ́wọ́ rẹ̀; o sì ti wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀. O ti gé ìgbà èwe rẹ̀ kúrú; o sì ti da ìtìjú bò ó. Yóo ti pẹ́ tó, OLUWA? Ṣé títí lae ni o óo máa fi ara pamọ́ fún mi? Yóo ti pẹ́ tó tí ibinu rẹ yóo máa jò bí iná? OLUWA, ranti bí ọjọ́ ayé ẹ̀dá ti gùn mọ, ati pé ẹ̀dá lásán ni ọmọ eniyan! Ta ló wà láyé tí kò ní kú? Ta ló lè gba ẹ̀mí ara rẹ̀ lọ́wọ́ agbára isà òkú? OLUWA, níbo ni ìfẹ́ rẹ ìgbàanì tí kì í yẹ̀ wà, tí o búra fún Dafidi pẹlu òtítọ́ rẹ? OLUWA, ranti bí èmi, iranṣẹ rẹ, ti di ẹni yẹ̀yẹ́; ati bí mo ti ń farada ẹ̀gàn àwọn eniyan, OLUWA àwọn ọ̀tá rẹ ń fi ẹni tí o fi àmì òróró yàn ṣe yẹ̀yẹ́, wọ́n sì ń kẹ́gàn ìrìn ẹsẹ̀ rẹ̀. Ẹni ìyìn ni OLUWA títí lae!
O. Daf 89:38-52 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni ààmì òróró rẹ. Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro. Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀. Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀. Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun. Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀. Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó. Yóò ti pẹ́ tó, OLúWA? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná? Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn! Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? OLúWA, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi? Rántí, OLúWA, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn, Ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, OLúWA, tí wọn gan ipasẹ̀ Ẹni ààmì òróró rẹ. Olùbùkún ní OLúWA títí láé. Àmín àti Àmín.