O. Daf 89:38-52

O. Daf 89:38-52 Yoruba Bible (YCE)

Ṣugbọn nisinsinyii inú rẹ ti ru sí ẹni àmì òróró rẹ; o ti ta á nù, o sì ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀. O ti pa majẹmu tí o bá iranṣẹ rẹ dá tì, o ti ba adé rẹ̀ jẹ́, o ti fi wọ́lẹ̀. O ti wó gbogbo odi rẹ̀; o sì ti sọ ilé ìṣọ́ rẹ̀ di ahoro. Gbogbo àwọn tí ń kọjá lọ ní ń kó o lẹ́rù; ó ti di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn aládùúgbò rẹ̀. O ti ran àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́; o ti mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ yọ̀ ọ́. Àní, o ti ba gbogbo ohun ìjà rẹ̀ jẹ́, o kò sì ràn án lọ́wọ́ lójú ogun. O ti gba ọ̀pá àṣẹ lọ́wọ́ rẹ̀; o sì ti wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀. O ti gé ìgbà èwe rẹ̀ kúrú; o sì ti da ìtìjú bò ó. Yóo ti pẹ́ tó, OLUWA? Ṣé títí lae ni o óo máa fi ara pamọ́ fún mi? Yóo ti pẹ́ tó tí ibinu rẹ yóo máa jò bí iná? OLUWA, ranti bí ọjọ́ ayé ẹ̀dá ti gùn mọ, ati pé ẹ̀dá lásán ni ọmọ eniyan! Ta ló wà láyé tí kò ní kú? Ta ló lè gba ẹ̀mí ara rẹ̀ lọ́wọ́ agbára isà òkú? OLUWA, níbo ni ìfẹ́ rẹ ìgbàanì tí kì í yẹ̀ wà, tí o búra fún Dafidi pẹlu òtítọ́ rẹ? OLUWA, ranti bí èmi, iranṣẹ rẹ, ti di ẹni yẹ̀yẹ́; ati bí mo ti ń farada ẹ̀gàn àwọn eniyan, OLUWA àwọn ọ̀tá rẹ ń fi ẹni tí o fi àmì òróró yàn ṣe yẹ̀yẹ́, wọ́n sì ń kẹ́gàn ìrìn ẹsẹ̀ rẹ̀. Ẹni ìyìn ni OLUWA títí lae!

O. Daf 89:38-52 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)

Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni ààmì òróró rẹ. Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro. Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀. Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀. Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun. Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀. Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó. Yóò ti pẹ́ tó, OLúWA? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná? Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn! Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? OLúWA, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi? Rántí, OLúWA, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn, Ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, OLúWA, tí wọn gan ipasẹ̀ Ẹni ààmì òróró rẹ. Olùbùkún ní OLúWA títí láé. Àmín àti Àmín.