Job 40:1-5
Job 40:1-5 Yoruba Bible (YCE)
OLUWA tún sọ fún Jobu pé, “Ṣé ẹni tí ń bá eniyan rojọ́ lè bá Olodumare rojọ́? Kí ẹni tí ń bá Ọlọrun jiyàn dáhùn.” Nígbà náà ni Jobu dá OLUWA lóhùn, ó ní: “OLUWA, kí ni mo jámọ́, tí n óo fi dá ọ lóhùn? Nítorí náà, mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́. Mo ti sọ̀rọ̀ ju bí ó ti yẹ lọ, n kò sì ní sọ̀rọ̀ mọ́.”
Job 40:1-5 Bibeli Mimọ (YBCV)
OLUWA da Jobu lohùn si i pẹlu, o si wipe, Ẹniti mba Olodumare jà, yio ha kọ́ ọ li ẹkọ́? ẹniti mba Ọlọrun wi, jẹ ki o dahùn! Nigbana ni Jobu da Oluwa lohùn, o si wipe: Kiyesi i, ẹgbin li emi; ohùn kili emi o da? emi o fi ọwọ mi le ẹnu mi. Ẹ̃kan ni mo sọ̀rọ̀, ṣugbọn emi kì yio si tun sọ mọ, lẹ̃meji ni, emi kò si le iṣe e mọ́.
Job 40:1-5 Yoruba Bible (YCE)
OLUWA tún sọ fún Jobu pé, “Ṣé ẹni tí ń bá eniyan rojọ́ lè bá Olodumare rojọ́? Kí ẹni tí ń bá Ọlọrun jiyàn dáhùn.” Nígbà náà ni Jobu dá OLUWA lóhùn, ó ní: “OLUWA, kí ni mo jámọ́, tí n óo fi dá ọ lóhùn? Nítorí náà, mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́. Mo ti sọ̀rọ̀ ju bí ó ti yẹ lọ, n kò sì ní sọ̀rọ̀ mọ́.”
Job 40:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
OLúWA dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé: “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!” Nígbà náà ni Jobu dá OLúWA lóhùn wá ó sì wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi. Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”