Esek 3:20
Esek 3:20 Bibeli Mimọ (YBCV)
Ẹ̀wẹ, nigbati olododo ba yipada kuro ninu ododo rẹ̀, ti o si da ẹ̀ṣẹ, ti mo si fi ohun idigbolu siwaju rẹ, yio kú; nitoriti iwọ kò kilọ fun u, yio kú ninu ẹ̀ṣẹ rẹ̀, a ki yio ranti ododo rẹ̀ ti o ti ṣe; ṣugbọn ẹjẹ rẹ̀ li emi o bere li ọwọ́ rẹ.
Esek 3:20 Yoruba Bible (YCE)
“Bẹ́ẹ̀ náà sì ni bí olódodo bá yipada kúrò ninu òdodo rẹ̀, tí ó bá dẹ́ṣẹ̀, tí mo sì gbé ohun ìkọsẹ̀ kan siwaju rẹ̀, yóo kú, nítorí pé o kò kìlọ̀ fún un, yóo kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a kò sì ní ranti iṣẹ́ òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe; ṣugbọn n óo bèèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ.
Esek 3:20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
“Bákan náà, bí olódodo kan bá yípadà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àìṣòdodo, tí mo sì fi ohun ìkọ̀sẹ̀ sí ọ̀nà rẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ kọ̀ láti kìlọ̀ fún un, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a ó gbàgbé gbogbo ìwà rere tó ti hù tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.