Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú Mat 1:23

Ìmọ́lẹ̀ Ayé - Ìfọkànsìn Adventi
Ọjọ́ Mẹ́rìn
Àràádọ́ta ọ̀kẹ́ àwọn Kristẹni kárí ayé ni yíò ṣe ayẹyẹ Kérésìmesì lọ́dún yìí. Adventi, ayẹyẹ àpẹẹrẹ tí ó ní ẹwà tí yíò yọrí sí Ọjọ́ Kérésìmesì, jẹ́ apákan ńlá ti àwọn ayẹyẹ Kérésìmesì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí o ṣe ń ka ìfọkànsìn Ìdánilẹ́kọ̀ọ́ tí Adventi yìí, ìwọ yóò ní ànfàní láti dara pọ̀ mọ́ra láti ṣe ayẹyẹ pẹ̀lú àwọn arákùnrin àti arábìnrin rẹ láti àwọn orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré, ìwọ ó sì kẹ́kọ̀ọ́ láti inú àwọn ojú ìwòye àti àwọn àṣà alágbára wọn.

Gbígbé nínú Jésù - Ètò-ẹ̀kọ́ Ìfọkànsìn Ọlọ́jọ́ Mẹ́rin lórí Ìwásáyé Jésù
Ọjọ́ Mẹ́rìn
Kérésìmesì ńbọ̀! Ó wá pẹ̀lú Ìwásáyé Jésù - ìmúrasílẹ̀ àti àjoyọ̀ ìbí Jésù. Sùgbọ́n njẹ́ ìmọ̀ yí kò ti sọnù nípasẹ̀ ìmúra ìsinmi ọdún, ríra ẹ̀bùn fún ọdún, tàbí ìgbàlejò àwọn ebí? Nínú lílọ sókè sódò àsìkò ọdún kérésìmesì, ní ìrírí titun nípa oríṣi ọ̀nà tí a lẹ gbà latí máa ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, èyí yíò sì fà ó súnmọ́ Ọlọ́run. Jí ọkàn rẹ dìde nínú ètò ọlọ́jọ́ mẹ́rin yìí láti inú àwọn àkójọ Bíbélì Gbé-Inú láti ọwọ́ Thomas Nelson.

Ẹ̀bùn Kérésìmesì
Ọjọ́ Mẹ́rìn
Kérésìmesì jẹ́ àkókò láti ṣe ayẹyẹ ẹ̀bùn tí ó ga jù lọ -Jésù Kristì. Tí a bá wo ìtàn nípa bí wọ́n ṣe ń retí pé kí Kristi dé ní ọjọ́ Kérésìmesì, ó máa ń rán wa l'étí pé Jésù wá láti jẹ́ ìmúṣẹ àwọn ìlérí àti ìdúróṣinṣin Ọlọ́run. Ní iwájú Jésù, Ìmánúẹ́lì, Ọlọ́run ńbẹ pẹ̀lú wa, ni ìrètí wa tí ń di ìmúṣẹ, tí àdúrà wa sì ti ń gbà.

Awọn itan keresimesi
Ọjọ́ 5
Gbogbo ìtàn gidi ló ní ìyípadà ìtàn - àkókò àìròtẹ́lẹ̀ tí ó yí gbogbo nǹkan padà. Ọ̀kan lára àwọn ìyípadà ìtàn tó tóbi jùlọ nínú Bíbélì ni ìtàn Kérésìmesì. Ní ọjọ́ márùn-ún tó ń bọ̀, a máa ṣàwárí bí ìṣẹ̀lẹ̀ kan yìí ṣe yí ayé padà àti bí ó ṣe lè yí ayé rẹ padà lónìí.

Gbogbo ohun wà ni ìparọ́rọ́: Gbígbà Jésù' Simi ni Kérésìmesì Èyí
Ọjọ marun
Ni àsìkò yìí láti wà ni onímùkẹ́ẹ̀kẹ̀, àmó tún n ṣiṣẹ́ lọ́wọ́ gan. Tẹ̀ lé mi ká lọ fún àkókò díè péré ti ìsimi àti sise ìjosìn tí o máa gbé o ró jákèjádò làálàá àríyá àsìkò náà. Tá gbé karí ìwé Mímú àwọn ewé odò kúrò ní Àwon Orúko Jésù: Bíbò Onífọkànsìn , Ètò kíkà onífọkànsìn ojó márùn-ún yìí yóò ṣamọ̀nà rè láti gbà Jésù’ simi ni Kérésìmesì nípa gbígbà àsìkò láti rántí dáradára Rè, fi áìní rè hàn, máa wá ìdákêjêjê Rè, áti gbékèlé pé olóòótọ́ Ni i.

Bí ìgbé ayé ṣe yí padà: Ní àkókò Kérésìmesì
Ọjọ 5
Nínú gbogbo ìgbòkègbodò ọdún, ó ṣeéṣe kí a má kíyèsára ìdí tí a fi ń ṣe ayẹyẹ. Nínú ètò ọlọ́jọ́ márùn bíbọ̀ Oluwa yí a ó ṣe àgbéyẹ̀wò àwọn ìlérí tí ìbí Rẹ̀ mú wá sí ìmúṣẹ nípa bí a ṣe bí Jésù àti ìrètí tí a ní fún ọjọ́ iwájú. Bí a ṣe ń kẹ́kọ̀ sí í nípa ẹni tí Ọlọ́run jẹ́, a ó ṣe àwárí bí a ṣe lè máa gbé ní àkókò ìsinmi ọdún pẹ̀lú ìrètí, ìgbàgbọ́, ayọ̀, àti àlàáfíà.

Bíbọ̀wá: Ìrìn Àjò Sí Kérésìmesì
Ojó Mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
Ìtàn Kérésìmesì jẹ́ èyí tó ní ọlá jùlọ lóòótọ́: èyí tó dá lóríi ìṣòótọ́ Ọlọ́run, agbára, ìgbàlà, àti ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn. Jẹ́ kí a lọ lórí ìrìn àjò ọlọ́jọ́ mẹ́ẹ̀dọ́ńgbọ̀n láti ṣe àwárí ètò pípé Ọlọ́run láti gba ayé lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti àwọn ìlérí tí a mú wá sí ìmúṣẹ nípa ìbí Ọmọ Rẹ̀.