Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú I. Pet 4:13

Líla Ìgbà Ìṣòro Kọjá
Ọjọ́ Mẹ́rin
A kò lè fẹ́ àwọn ìdojúkọ kù nínú ayé wa. Ṣùgbọ́n nínú Ètò kúkúrú ọlọ́jọ́-4 yìí, a ó máa gbà wá ní ìyànjú láti mọ̀ pé a kò dá nìkan wà, pé Ọlọ́run ní ète fún ìrora wa, àti pé yíó lò ó fún ètò gíga Rẹ̀.

Ọ̀nà Ìjọba náà
Ojọ́ Márùn-ún
Ọlọ́run ń sọ ìjọ Rẹ̀ jí, a sì ní láti rí àkópọ̀ ìṣe Rẹ̀ yìí. Ní ìgbà tí ǹǹkan bá nira, ó maá ń ṣe wá bíi kí a j'áwọ́. Ẹ̀wẹ̀, ìgbà yìí kìí ṣe àsìkò tí a lè j'áwọ́. Da ara pọ̀ mọ́ wa bí a ó ṣe máa kà nípa àsìkò tí a wà, àti bí a ó ṣe mọ àwọn ìgbésẹ̀ tí a ó gbé láti dúró kí a sì mú Ìjọba Ọlọ́run gbòòro sí í.

1 Peteru
5 Awọn ọjọ
Nípa ìrètí rẹ̀ nínú lẹ́tá tí ó ko sí ìjọ àkọ́kọ́, Peteru gbà wá níyànjú kí a ní ìgbàgbọ́, kí á sì gbọ́ràn. Ó ní kí á dúró sinsin nínú ìgbàgbọ́ nígbà tí a bá ń kojú àdánwò àti inúnibíni. Ó ní nítorí ẹ̀dá tí a jẹ́ nínú Jésù, a ní agbára láti gbé ìgbá ayé ìwà mímọ́, a ó sì le ní àfojúsùn ogún ayérayé.