Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú I. Kor 10:31

Bọ́ Sínú Ìgbésí Ayé Tó Ní Ìtumọ̀
Ọjọ́ márùn-ún
Kí ni kókó ìwàláàyè mi? Kí ni ǹkan tí a dá mi láti gbé ṣe? Kíni ètò Ọlọ́run fún mi? Wọ̀nyí ni àwọn ìbéèrè tí púpọ̀ nínú wa ma ń bèrè nígbà kan tàbí òmíràn ní ìgbésí ayé wa. Ìlépa wa ni láti ṣe ìtúpalẹ̀ ohun tí a nílò láti ṣe fún ipa àti láti ní ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè náà. Darapọ̀ mọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ìwé gíga ti C3 bí wọ́n ti ń tan ìmọ́lẹ̀ sí kókó náà.

Ṣíṣe Okoòwò L'ọ́nà T'ẹ̀mí
Ọjọ́ mẹ́fà
Mo gba irọ́ kan gbọ́ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún. Irọ́ yìí wọ́pọ̀ l'ágbo Krìstìẹ́nì. Mo gbàgbọ́ nínú ìyàtọ̀ láàrin ohun tí kò jẹ mọ́ ẹ̀sìn àti ohun-mímọ́. Èyí fà mí sẹ́hìn gidi. D'arapọ̀ mọ́ mi láti ṣe àgbéyẹ̀wò bi Ọlọ́run ṣe fẹ́ẹ́ fí okun ẹ̀mí kún wa láti mú Ọ̀run wá sínú Ayé yìí àti láti ṣe àṣeyọrí nínú okoòwò atí ìgbé-ayé. A ní ànfààní púpọ̀ láti la ipa nínú ayé ju àwọn "òjíṣẹ́ Ọlọ́run orí ìjọ" lọ, ìlànà Bíbélì yìí yíò fi bóo ti rìn hàn ọ́!