Ọbadiah Ìfáàrà
Ìfáàrà
Ọbadiah ìránṣẹ́ Olúwa sọ nípa ìṣubú tó ń bọ̀ wá sórí Edomu. Ó jẹ́ kí a rí i pé Edomu gbéraga lórí ààbò rẹ̀. Níwọ́n ìgbà tí Edomu ti ṣe èyí, wọn ṣe ohun tó burú níwájú Olúwa, Ọlọ́run sì mú ìbínú wa sórí wọn. Olúwa wí pé òun yóò pa wọ́n run, ṣùgbọ́n òun yóò gba orí òkè Sioni àti Israẹli là, ìjọba Ọlọ́run yóò sì fi ẹsẹ̀ múlẹ̀.
Kókó kan pàtàkì ti ìwé yìí fẹ́ kí a mọ́ ní pe, Edomu kùnà pátápátá, wọn kò ran Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì dá ìjà sílẹ̀. Nítorí pé Ọlọ́run kọ Esau, kò sì ṣí ọ̀nà tí yóò fi gbé àwọn ọmọ Edomu ga. Edomu sá wọ inú òkè agbára lọ, wọn kì yóò sì ní ibùgbé. Ṣùgbọ́n Israẹli yóò ṣe rere nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
Kókó-ọ̀rọ̀
i. Àkọlé àti ìbẹ̀rẹ̀ 1.
ii. Ìdájọ́ lórí Edomu 2-14.
iii. Ọjọ́ Olúwa 15-21.
Currently Selected:
Ọbadiah Ìfáàrà: YCB
Highlight
Share
Copy
Want to have your highlights saved across all your devices? Sign up or sign in
Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní
Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc.
A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé.
Yoruba Contemporary Bible
Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.®
Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.