YouVersion Logo
Search Icon

ÌWÉ ÒWE 21

21
1Orísun omi ni ọkàn ọba lọ́wọ́ OLUWA,
ibi tí ó bá wu Oluwa ni ó ń darí rẹ̀ sí.
2Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó dára lójú ara rẹ̀,
ṣugbọn ọkàn ni OLUWA ń wò.
3Kí eniyan ṣe òdodo ati ẹ̀tọ́,
sàn ju ẹbọ lọ lójú OLUWA.
4Bíi fìtílà ẹni ibi ni gbígbé ojú gangan ati ìgbéraga,
ẹ̀ṣẹ̀ sì ni wọ́n.
5Dájúdájú èrò ẹni tí ó ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn yóo yọrí sí ọ̀pọ̀,
ṣugbọn ẹni tí ó bá ń kánjú jù kò ní ní ànító.
6Fífi èké kó ìṣúra jọ
dàbí lílé ìkùukùu, ó sì jẹ́ tàkúté ikú.
7Ìwà ipá àwọn ẹni ibi ni yóo gbá wọn dànù,
nítorí pé wọ́n kọ̀ láti ṣe òtítọ́.
8Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún,
ṣugbọn ìrìn aláìlẹ́bi a máa tọ́.
9Ó sàn láti máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà,#Sir 25:16
ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.
10Ibi ni ọkàn eniyan burúkú máa ń fẹ́,
àwọn aládùúgbò rẹ̀ kì í sìí rí ojurere rẹ̀.
11Ìjìyà ẹlẹ́yà a máa mú kí òpè gbọ́n,
tí a bá ń kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo ní ìmọ̀ sí i.
12Olódodo ṣàkíyèsí ilé eniyan burúkú,
eniyan burúkú sì bọ́ sinu ìparun.
13Ẹni tí ó kọ etí dídi sí igbe talaka,
òun náà yóo kígbe, ṣugbọn kò ní rí ẹni dá a lóhùn.
14Ẹ̀bùn tí a fúnni ní kọ̀rọ̀ a máa paná ibinu,
àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a tì bọ abẹ́ aṣọ a máa paná ìjà.
15Tí a bá ṣe ìdájọ́ òtítọ́, inú olódodo a dùn,
ṣugbọn ìfòyà ni fún àwọn aṣebi.
16Ẹni tí ó sá kúrò lọ́nà òye
yóo sinmi láàrin àwọn òkú.
17Ẹni tí ó fẹ́ràn fàájì yóo di talaka,
ẹni tí ó fẹ́ràn ọtí waini ati òróró kò ní lówó lọ́wọ́.
18Eniyan burúkú ni yóo forí gba ibi
tíì bá dé bá olódodo.
Alaiṣootọ ni yóo fara gba ìyà tí ó tọ́ sí olóòótọ́ inú.
19Ó sàn láti máa gbé ààrin aṣálẹ̀,
ju kí eniyan máa bá oníjà ati oníkanra obinrin gbé lọ.
20Ní ilé ọlọ́gbọ́n ni à á tí ń bá nǹkan olówó iyebíye,
ṣugbọn òmùgọ̀ a máa ba tirẹ̀ jẹ́.
21Ẹni tí ń lépa òdodo ati àánú
yóo rí ìyè, òdodo, ati iyì.
22Ọlọ́gbọ́n a máa gba ìlú àwọn alágbára
a sì wó ibi ààbò tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé lulẹ̀.
23Ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́
pa ara rẹ̀ mọ́ kúrò ninu ìyọnu.
24“Oníyẹ̀yẹ́” ni orúkọ ẹni tí ń gbéraga,
tí ó sì ń ṣe mo tó báyìí-dà báyìí.
25Ìrònú ohun tí ọ̀lẹ fẹ́ ni yóo pa á,
nítorí ọwọ́ rẹ̀ kọ̀ láti ṣiṣẹ́.
26Eniyan burúkú a máa ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ìgbà,
ṣugbọn olódodo ń fúnni láìdáwọ́dúró.
27Ohun ìríra ni ẹbọ eniyan burúkú,#Sir 7:9
pàápàá tí ó bá mú un wá pẹlu èrò ibi.
28Ọ̀rọ̀ ẹlẹ́rìí èké yóo di asán,
ṣugbọn ọ̀rọ̀ ẹni tí ó fetí sílẹ̀ ni a óo gbàgbọ́.
29Eniyan burúkú a máa lo ògbójú,
ṣugbọn olóòótọ́ máa ń yẹ ọ̀nà ara rẹ̀ wò.
30Kò sí ọgbọ́n, tabi òye, tabi ìmọ̀,
tí ó lè dojú kọ OLUWA kí ó mókè.
31Eniyan a máa tọ́jú ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun,
ṣugbọn OLUWA ló ni ìṣẹ́gun.

Currently Selected:

ÌWÉ ÒWE 21: YCE

Highlight

Share

Copy

None

Want to have your highlights saved across all your devices? Sign up or sign in