1
Òwe 3:5-6
Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní
Gbẹ́kẹ̀lé OLúWA pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ; Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
Compare
Explore Òwe 3:5-6
2
Òwe 3:7
Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ bẹ̀rù OLúWA kí o sì kórìíra ibi.
Explore Òwe 3:7
3
Òwe 3:9-10
Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún OLúWA, pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ Nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
Explore Òwe 3:9-10
4
Òwe 3:3
Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
Explore Òwe 3:3
5
Òwe 3:11-12
Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí OLúWA má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí, Nítorí OLúWA a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
Explore Òwe 3:11-12
6
Òwe 3:1-2
Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi. Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ. Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà, ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
Explore Òwe 3:1-2
7
Òwe 3:13-15
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀, ẹni tí ó tún ní òye sí i Nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ. Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ; kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
Explore Òwe 3:13-15
8
Òwe 3:27
Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ, nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
Explore Òwe 3:27
9
Òwe 3:19
Nípa ọgbọ́n, OLúWA fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn
Explore Òwe 3:19
Home
Bible
Plans
Videos